The Noble Qur'an Encyclopedia
Towards providing reliable exegeses and translations of the meanings of the Noble Qur'an in the world languagesThose who drag forth [An-Naziat] - Yoruba translation
Surah Those who drag forth [An-Naziat] Ayah 46 Location Maccah Number 79
Allāhu fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́ búra.
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo búra.
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀ búra.
Ó tún fi àwọn mọlāika tó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà búra.
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń ṣètò nínú sánmọ̀ àti ilé ayé pẹ̀lú àṣẹ Allāhu búra.
Ní ọjọ́ tí ìmìtìtì máa mi gbogbo ayé tìtì.[1]
Ohun tí ó máa tẹ̀lé e máa ṣẹlẹ̀ tẹ̀lé e.[1]
Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.
Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.
Wọn yóò wí pé: “Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?
Ṣé nígbà tí a ti di eegun tó kẹfun tán?”
Wọ́n wí pé: “Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni tó pè é ní irọ́.)”
Nítorí náà, igbe ẹyọ kan sì ni.
Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.
Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonúfojì mímọ́, Tuwā.
Lọ bá Fir‘aon, dájúdájú ó ti tayọ ẹnu-ààlà.
Kí o sì sọ pé: “Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?
Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, kí o sì páyà (Rẹ̀).”
Ó sì fi àmì tó tóbi hàn án.
(Àmọ́) ó pè é ní òpùrọ́. Ó sì yapa (rẹ̀).
Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).
Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.
Ó sì wí pé: “Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ.”
Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).[1]
Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni tó ń páyà (Allāhu).
Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?
Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé tó gún régé.
Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.
Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.[1]
Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.
Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.
Ìgbádùn ni fún yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìparun ńlá bá dé,
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun tó ṣe níṣẹ́.
Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni tó ríran.
Nítorí náà, ní ti ẹni tó tayọ ẹnu-ààlà,
tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,
dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Ní ti ẹni tí ó páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),
dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: “Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?”
Níbo ni ìwọ wà sí ìmọ̀ rẹ̀ ná?[1]
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.
Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni tó ń páyà rẹ̀.
Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò gbé ilé ayé tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan.