عربيEnglish

The Noble Qur'an Encyclopedia

Towards providing reliable exegeses and translations of the meanings of the Noble Qur'an in the world languages

The Most High [Al-Ala] - Yoruba translation

Surah The Most High [Al-Ala] Ayah 19 Location Maccah Number 87

Ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni gíga jùlọ.

Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá. Ó sì ṣe (oríkèé-ríkèé rẹ̀) ní dọ́gbadọ́gba.

Ẹni tí Ó yan kádàrá (fún ẹ̀dá). Ó sì tọ́ ọ sọ́nà.[1]

Ẹni tí Ó mú koríko tútù hù jáde,

Ó sì sọ ọ́ di gbígbẹ tó dúdú.

Àwa yóò máa ké (al-Ƙur’ān) fún ọ. Ìwọ kò sì níí gbàgbé.

Àyàfi ohun tí Allāhu bá fẹ́.[1] Dájúdájú Ó mọ gban̄gba àti ohun tó pamọ́.

Àwa yó sì ṣe iṣẹ́ rere ní ìrọ̀rùn fún ọ.

Nítorí náà, ṣèrántí ní àyè tí ìrántí ti wúlò.[1]

Ẹni tí ó máa páyà (Allāhu) máa lo ìrántí.

Olórí-burúkú sì máa takété sí i.

(Òun sì ni) ẹni tí ó máa wọ inú Iná tó tóbi.

Lẹ́yìn náà, kò níí kú sínú rẹ̀, kò sì níí ṣẹ̀mí (àlàáfíà).

Dájúdájú ẹni tí ó bá ṣe àfọ̀mọ́ (ẹ̀sìn rẹ̀) ti jèrè.[1]

Ó sì rántí orúkọ Olúwa rẹ̀, ó sì kírun.

Rárá, ńṣe l’ẹ̀ ń gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé.

Ọ̀run sì lóore jùlọ, ó sì máa wà títí láéláé.

Dájúdájú èyí wà nínú àwọn tákàǹdá àkọ́kọ́,

tákàdá (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm àti (Ànábì) Mūsā.