عربيEnglish

The Noble Qur'an Encyclopedia

Towards providing reliable exegeses and translations of the meanings of the Noble Qur'an in the world languages

The morning hours [Ad-Dhuha] - Yoruba translation

Surah The morning hours [Ad-Dhuha] Ayah 11 Location Maccah Number 93

Allāhu fi ìyálẹ̀ta búra.

Ó tún fi alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú búra.

Olúwa rẹ kò pa ọ́ tì, kò sì bínú sí ọ.

Dájúdájú láìpẹ́ Olúwa rẹ máa fún ọ ní (oore púpọ̀ ní ọ̀run). Nítorí náà, o sì máa yọ́nú sí i.

Ṣé (Allāhu) kò rí ọ ní ọmọ-òrukàn ni? Ó sì fún ọ ní ibùgbé.

Ó sì rí ọ ní aláìmọ̀nà (ìyẹn ṣíwájú ìsọ̀kalẹ̀ ìmísí). Ó sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́.[1]

Ó tún rí ọ ní aláìní, Ó sì rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀.

Nítorí náà, ní ti ọmọ-òrukàn, má ṣe jẹ gàba (lé e lórí).

Ní ti alágbe, má sì ṣe jágbe (mọ́ ọn).

Ní ti ìdẹ̀ra Olúwa rẹ, sọ ọ́ jáde.