The Noble Qur'an Encyclopedia
Towards providing reliable exegeses and translations of the meanings of the Noble Qur'an in the world languagesThe morning hours [Ad-Dhuha] - Yoruba translation
Surah The morning hours [Ad-Dhuha] Ayah 11 Location Maccah Number 93
Allāhu fi ìyálẹ̀ta búra.
Ó tún fi alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú búra.
Olúwa rẹ kò pa ọ́ tì, kò sì bínú sí ọ.
Dájúdájú ọ̀run lóore fún ọ ju ayé.
Dájúdájú láìpẹ́ Olúwa rẹ máa fún ọ ní (oore púpọ̀ ní ọ̀run). Nítorí náà, o sì máa yọ́nú sí i.
Ṣé (Allāhu) kò rí ọ ní ọmọ-òrukàn ni? Ó sì fún ọ ní ibùgbé.
Ó sì rí ọ ní aláìmọ̀nà (ìyẹn ṣíwájú ìsọ̀kalẹ̀ ìmísí). Ó sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́.[1]
Ó tún rí ọ ní aláìní, Ó sì rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀.
Nítorí náà, ní ti ọmọ-òrukàn, má ṣe jẹ gàba (lé e lórí).
Ní ti alágbe, má sì ṣe jágbe (mọ́ ọn).
Ní ti ìdẹ̀ra Olúwa rẹ, sọ ọ́ jáde.